9. Nísinsìn yìí àwọn ará Fílístínì ti wá láti gbógun ti àfonífojì Réfáímù;
10. Dáfídì sì béèrè lọ́dọ̀ Ọlọ́run wí pé: “Kí èmi kí ó gòkè tọ àwọn ará Fílístínì lọ bí? Ìwọ ó ha fi wọ̀n lé mi lọ́wọ́?” Olúwa sì wí fún un pé, “Gòkè lọ èmi ó sì fi wọ́n lé ọ lọ́wọ́.”
11. Bẹ́ẹ̀ ni Dáfídì àti àwọn ènìyàn Rẹ̀ gòkè lọ sí Baali-Pérásímù, níbẹ̀ ó sì kọlù wọ́n. Ó sí wí pé, “Gẹ́gẹ́ bí omi tí ya jáde, Ọlọ́run ti ya Dáfídì lórí àwọn ọ̀ta mi pẹ̀lú ọwọ́ mi.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì ń pè ibẹ̀ ní Baali-Pérásímù.